Ísíkẹ́lì 23:13-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.

14. “Ṣùgbọ́n ó tẹ̀ ṣíwájú nínú ṣíṣe aṣẹ́wó. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kálídíà àwòrán púpa,

15. pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Bábílónì ọmọ ìlú Kálídíà.

16. Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán onísẹ́ sí wọn ni Kálídíà.

17. Àwọn ará Bábílónì wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ìbùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúùfẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú.

Ísíkẹ́lì 23