Ísíkẹ́lì 16:6-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. “ ‘Nígbà tí mo sì kọjá tí mo rí ọ tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ, mo sọ fún ọ pé, “Yè!”

7. Mo mú ọ dàgbà bí ohun ọ̀gbìn inú oko. O ga sókè, o sì dàgbà, o wá di arẹwà jùlọ, ọmú rẹ yọ, irun rẹ gùn, ìwọ tí o wà ní ìhòòhò láì fi nǹkan kan bora.

8. “ ‘Nígbà tí mo tún kọjá, tí mo rí ọ, mo rí i pé àsìkò àti nífẹ́ rẹ ti tó, mo fi iṣẹtí aṣọ mi bo ìhòòhò rẹ. Mo jẹ́jẹ̀ẹ́ fún ọ mo sì bá ọ dá májẹ̀mú láti di tèmi, ni Olúwa Ọlọ́run wí,

9. “ ‘Nígbà náà ni mo fi omi wẹ ẹ̀jẹ̀ kúrò lára rẹ, mo fi ìpara pa ọ́ lára.

10. Mo fi aṣọ oníṣẹ́ ọ̀nà sí ọ lára láti wọ̀ ọ́, mo wọ bàtà aláwọ fún ọ. Mo fi aṣọ funfun lẹlẹ àti aṣọ olówó iyebíye ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́.

11. Mo fi ohun ọ̀ṣọ́ ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́, mo fi ẹ̀gbà ọwọ́ sí ọ lọ́wọ́, mo fi ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn sí ọ lọ́rùn,

12. Mo sì tún fi òrùka sí ọ nímú, mo fi yẹtí sí ọ létí, mo sì fi adé tó rẹwà dé ọ lórí.

Ísíkẹ́lì 16