Ísíkẹ́lì 16:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:

2. “Ọmọ ènìyàn, mú kí Jérúsálẹ́mù mọ gbogbo ìwà ìríra rẹ̀.

3. Sọ pé, ‘Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run wí sí Jérúsálẹ́mù: Ìran rẹ àti ilẹ̀ ìbí rẹ wà ní ilẹ̀ Kénáànì; ará Ámórì ni baba rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ ará Hítì.

4. Ní ọjọ́ tí a bí ọ, a kò gé okùn ìwọ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fomi wẹ̀ ọ́ láti mú kí o mọ́, tàbí ká fiyọ̀ pa ọ́ lára tàbí ká fi aṣọ wé ọ.

5. Kò sẹ́ni tó ṣàánú tàbí kẹ́dùn rẹ débi àtiṣe ikankan nínú iwọ́nyi fún ọ ṣùgbọ́n lọ́jọ́ ìbí rẹ, ìta la jù ọ́ sí torí wọ́n kórìíra rẹ.

Ísíkẹ́lì 16