8. Ẹ bẹ̀rù idà, n ó sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
9. N ó lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, n ó sì fà yín lé àlejò lọ́wọ́, n ó sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
10. Nípa idà ni ẹ ó ṣubú, n ó sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Ísírẹ́lì. Nígbà náà lẹ ó mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.
11. Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀; N ó ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Ísírẹ́lì.
12. Ẹ̀yin ó sì mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀ èdè tó yí yín ká.”
13. Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pélátíà ọmọ Bénáyà kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Áà! Olúwa, Ọlọ́run! Ṣé o fẹ́ pa ìyókù Ísírẹ́lì run pátapáta ni?”
14. Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá: