Ìfihàn 16:3-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Èkejì sì tú ìgò sínú òkun; ó sì dàbí ẹ̀jẹ̀ òkú ènìyàn: gbogbo ọkàn alàyè sì kú nínú òkun.

4. Ẹ̀kẹ́ta sì tú ìgò tirẹ̀ sínú odò, àti sí orísun àwọn omi; wọ́n sì di ẹ̀jẹ̀.

5. Mo sì gbọ́ ańgẹ́lì ti omi wí pé:“Olódodo ni ìwọ Ẹni Mímọ́ ẹni tí ó ń bẹ,tí ó sì ti wà,nítorí tí ìwọ ṣe ìdájọ́ báyìí.

6. Nítorí tí wọ́n ti ta ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn mímọ́ àti ti àwọn wòlíì sílẹ̀,ìwọ sì fi ẹ̀jẹ̀ fún wọn mu; èyí yìí ní ó yẹ wọ́n.”

7. Mo sì gbọ́ pẹpẹ ń ké wí pé:“Bẹ́ẹ̀ ni, Olúwa Ọlọ́run Olódùmarè,òtítọ́ àti òdodo ní ìdájọ́ rẹ.”

Ìfihàn 16