1. Sọ́ọ̀lù sì wà níbẹ̀, ó sì ní ohùn sí ikú rẹ̀.Ní àkókò náà, inúnibini ńlá kan dìde sí ìjọ tí ó wà ni Jerúsálémù, gbogbo wọn sì túká káàkiri agbègbè Jùdíà àti Samaríà, àyàfi àwọn àpósítélì.
2. Àwọn ènìyàn olùfọkànsìn kan sì gbé òkú Sítéfánù lọ sin, wọ́n sì pohùnréré ẹkún kíkan sórí rẹ̀.