Ìṣe Àwọn Àpósítélì 28:8-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Ó sì ṣe, baba Pọ́bílíù dubulẹ àìsàn ibà àti ìgbẹ́-ọ̀rìn; ẹni tí Pọ́ọ̀lù wọlé tọ̀ lọ, tí ó sì gbàdúrà fún, nígbà tí ó sì fi ọwọ́ lé e, ó sì mú un láradá.

9. Nígbà tí èyí sì ṣe tán, àwọn ìyókù tí ó ni àrùn ni erékùṣù náà tọ̀ ọ́ wá, ó sì mú wọn láradá.

10. Wọ́n sì bu ọlá púpọ́ fún wa; nígbà tí a ń lọ, wọ́n sì fún wa ní ohun púpọ̀ tí a nílò ní ọ̀nà àjò wa.

11. Lẹ́yìn oṣù mẹ́ta, a wọ ọkọ̀ ojú-omi kan èyí tí ó lo àkókò otútù ní erékùsù náà. Ó jẹ́ ọkọ̀ ojú-omi ti Alekisáńdírà, èyí tí ó àmì èyí tí se òrìsà ìbejì ti Kásítórù òun Pólúkísù.

12. Nígbà tí a sì gúnlẹ̀ ní Sírákúsì, a gbé ibẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta.

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 28