25. Ṣùgbọ́n èmi rí i pé, kò se ohun kan tí ó yẹ sí ikú, bí òun tìkárarẹ̀ sí tí fi ọ̀ràn rẹ̀ lọ Aúgọ́sítù, mo tí pinnu láti rán an lọ.
26. Ṣùgbọ́n èmi kò ri ohun kan dájúdájú láti kọ̀wé sí olúwa mi. Nítorí náà ni mo ṣe mú un jáde wá ṣíwájú yín, àní ṣíwájú rẹ ọba Àgírípà, kí o fi jẹ́ pé lẹ́yìn tí a ba tí se wádìí rẹ̀, èmi yóò lè rí ohun tí èmi yóò kọ.
27. Nítorí tí kò tọ́ ní ojú mi láti rán òǹdè, kí a má sì sọ ọ̀ràn tí a kà sí i lọ́rùn.”