1. Nígbà ti Àpólò wà ni Kọ́ríńtì, ti Pọ́ọ̀lù kọjá lọ sí apá òkè-ìlú, ó sì wá ṣí Éfésù: o sì rí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn kan;
2. Ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ha gba Ẹ̀mi Mímọ́ náà nígbà tí ẹ̀yin gbàgbọ́?”Wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa kò gbọ́ rárá pé Ẹ̀mí Mímọ́ kan wà.”
3. Ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ irú bamítíìsímù wo ni a bamitíìsímù yín sí?”Wọ́n sì wí pé, “Sí bamitíìsímù tí Jòhánù.”