20. Nígbà tí wọ́n sì bẹ̀ ẹ́ pé, kí ó bá àwọn jókòó díẹ̀ sí i, ó kọ̀;
21. Ṣùgbọ́n ó dágbére fún wọn, ó sì wí pé, (Èmi kò gbọdọ̀ má ṣe àjọ ọdún tí ń bọ̀ yìí ni Jerúsálémù bí ó tí wù kí ó rí: ṣùgbọ́n) “Èmi ó tún padà tọ̀ yín wá, bí Ọlọ́run bá fẹ́.” Ó sì ṣíkọ̀ láti Éfésù.
22. Nígbà tí ó sì tí gúnlẹ̀ ni Keṣaríà; tí ó gòkè, tí ó sì kí ijọ, ó sọ̀kalẹ̀ lọ sì Áńtíókù.
23. Nígbà tí ó sì gbé ọjọ́ díẹ̀ níbẹ, ó lọ, ó sì kọjá lọ láti Gálátíà àti Fírígíà, ó mú gbogbo àwọn ọmọ-ẹ̀yìn lọ́kàn le.
24. Júù kan sì wà tí a ń pè ni Àpólò, tí a bí ni Alekisáńdíríà, ó wá sí Éféṣù. Ó nì ẹ̀bùn ọ̀rọ̀-sísọ, ó sì mọ ìwé mímọ́ púpọ̀;