Ìṣe Àwọn Àpósítélì 15:16-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. “ ‘Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni èmi ó padà,èmi ó sì tún àgọ́ Dáfídì pa tí ó ti wó lulẹ̀:èmi ó sì tún ahoro rẹ̀ kọ́,èmi ó sì gbé e ró:

17. kí àwọn ènìyàn ìyókù lè máa wá Olúwa,àti gbogbo àwọn aláìkọlà tí a ń fi orúkọ mi pè.’ni Olúwa wí, ta ni ó ń ṣe nǹkan wọ̀nyí

18. Ní Olúwa wí, ẹni tí ó sọ gbogbonǹkan wọ̀nyí di mímọ́ láti ọjọ́ pípẹ́ wá,

19. “Ǹjẹ́ ìmọ̀ràn tèmi ni pé, kí a máa ṣe yọ àwọn ti aláìkọlà ti ó yípadà sí Ọlọ́run lẹ́nu.

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 15