Hósíà 14:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Yípadà ìwọ Ísírẹ́lì sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.Ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ló fa ìparun rẹ!

2. Ẹ gba ọ̀rọ̀ Olúwa gbọ́,Kí ẹ sì yípadà sí Olúwa.Ẹ sọ fún un pé:“Darí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wákí o sì fi oore ọ̀fẹ́ gbà wá,kí àwa kí ó lè fí ètè wa sán-an fún ọ

3. Asíríà kò le gbà wá là;A kò ní í gorí ẹsin ogunA kò sì ní tún sọ ọ́ mọ́ láé‘Àwọn ni òrìṣà wasí àwọn ohun tí ó fi ọwọ́ wa ṣe;nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ ni àwọnaláìní baba tí ń rí àánú.’

4. “Èmi wo àgàbàgebè wọn sàn,Èmi ó sì fẹ́ràn wọn, lọ́fẹ̀ẹ́,nítorí ìbínú mi ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ọ wọn.

5. Èmi o dàbí ìrì sí Ísírẹ́lìwọn o sì yọ ìtànná bi ewéko lílìyóò sì ta gbòngbòkédárì ti Lébánónì

6. Àsẹ̀sẹ̀yọ ẹ̀ka rẹ̀ yóò dàgbà,Didan ẹwà yóò rẹ̀ dànù bí igi ólífìÒórùn rẹ yóò sì dàbí igi sídà ti Lébánónì.

Hósíà 14