1. Ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù keje, ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípaṣẹ̀ wòlíì Hágáì wí pé:
2. “Sọ fún Sérúbábélì ọmọ Séítélì, olórí Júdà, àti Jóṣúà ọmọ Jósédékì, olórí àlùfáà àti àwọn ènìyàn yòókù. Béèrè lọ́wọ́ wọn pé,
3. ‘Ta ni nínú yín tí ó kù tí ó sì ti rí ilé yìí ní ògo rẹ̀ àkọ́kọ́? Báwo ni ó ṣe ri sí yín nísinsin yìí? Ǹjẹ́ kò dàbí asán lójú yín?
4. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, múra gírí, ìwọ Sérúbábélì,’ ni Olúwa wí. ‘Múra gírí, ìwọ Jóṣúà ọmọ Jósédékì, olórí àlùfáà. Ẹ sì múra gírí gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ilẹ̀ náà;’ ni Olúwa wí, ‘kí ẹ sì ṣiṣẹ́. Nítorí èmi wà pẹ̀lú yín;’ ni Olúwa àwọn ọmọ ogun wí.
5. ‘Èyí ni ohun tí Èmi fi bá a yín dá májẹ̀mú nígbà tí ẹ jáde kúrò ní Éjíbítì, bẹ́ẹ̀ ni Ẹ̀mí ì mi sì wà pẹ̀lú yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù.’
6. “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Láìpẹ́ jọjọ, Èmi yóò mi àwọn ọrun àti ayé, òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.