Hábákúkù 3:3-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ọlọ́run yóò wa láti Témánì,Ibi mímọ́ jùlọ láti Òkè Páránìògo rẹ̀ sí bo àwọn ọ̀run,Ilé ayé sì kún fún ìyìn rẹ

4. Dídán rẹ ṣí dàbí ìmọ́lẹ̀;Ìmọ́lẹ̀ kọ-ṣàn-án láti ọwọ́ rẹ wá,níbi tí wọn fi agbára rẹ̀ pamọ́ sí.

5. Àjàkálẹ̀ àrùn ń lọ ni iwájú rẹ;ìyọnu ṣí ń tọ ẹsẹ̀ rẹ lọ.

6. Ó dúró, ó sì mi ayé;ó wò, ó sì mú àwọn orílẹ̀-èdè wárìrìa sì tú àwọn òkè-ńlá ayérayé ká,àwọn òkè kéékèèkéé ayérayé sì tẹríba:ọ̀nà rẹ ayérayé ni.

7. Mo rí àgọ́ Kúṣánì nínú ìpọ́njúàti àwọn ibùgbé Mídíanì nínú ìrora.

Hábákúkù 3