Hábákúkù 1:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ìran tí wòlíì Hábákúkù rí.

2. Olúwa, emì yóò ti ké pẹ́ tó fún ìrànlọ́wọ́,Ṣùgbọ́n ti ìwọ kò ni fetí sí mi?Tàbí kígbe sí ọ ní ti, “Ìwà ipá!”ṣùgbọ́n tí ìwọ kò sì gbàlà?

3. Èéṣe tí ìwọ fi mú mi rí àìṣedéédéÈéṣe tí ìwọ sì fààyè gba ìwà ìkà?Ìparun àti ìwà ipá wà ní iwájú mi;ìjà ń bẹ, ìkọlù sì wà pẹ̀lú.

4. Nítorí náà, òfin di ohun àìkàsí,ìdájọ́ òdodo kò sì borí.Àwọn ẹni búburú yí àwọn olódodo ká,Nítorí náà ni ìdájọ́ òdodo ṣe yí padà

Hábákúkù 1