Gálátíà 3:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ẹ̀yin aláìnírònú ará Gálátíà! ta ní ha tàn yín jẹ, kí ẹ̀yin má ṣe gba òtítọ́ gbọ́? Ní ojú ẹni tí a fi Jésù Kírísítì hàn gbangba láàrin yín ni ẹni tí a kàn mọ́ àgbélébùú.

2. Kìkì èyí ni mo fẹ́ bèèrè lọ́wọ́ yín: Nípa iṣẹ́ òfin ni ẹ̀yin gba Ẹ̀mi bí, tàbí nípa ìgbọ́ràn pẹ̀lú ìgbàgbọ́?

3. Báyìí ni ẹ̀yin ṣe gọ̀ tó bí? Lẹyin tí ẹ bẹ̀rẹ̀ nípa tí Ẹ̀mí, a há ṣe yín pé nísinsìnyìí nípa tí ara?

4. Ẹ̀yin ha ti jìyà ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan wọ̀nyí lásán? Bí ó bá ṣe pé nítoótọ́ lásán ni.

5. Ṣé Ọlọ́run fún yín ní Ẹ̀mí rẹ̀, tí ó sì ṣe iṣẹ́-ìyanu láàrin yín nítorí tí ẹ̀yin pa òfin mọ, tàbí nítorí ẹ ní ìgbàgbọ sí ohun tí ẹ gbọ́?

6. Gẹ́gẹ́ bí Ábúráhámù “Ó gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí fún un ní òdodo.”

7. Ẹ jẹ́ kí ó yé é yín nígbà náà pé, àwọn ti ó gbàgbọ́, àwọn náà ní í ṣe ọmọ Ábúráhámù.

8. Bí ìwé-mímọ́ sì tí wí tẹ́lẹ̀ pé, Ọlọ́run yóò dá aláìkọlà láre nípa ìgbàgbọ́, ó tí wàásù ìyìn rere ṣáájú fún Ábúráhámù, ó ń wí pé, “Nínú rẹ̀ ni a ó bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè.”

Gálátíà 3