8. Nítorí Ọlọ́run, ẹni tí ó ṣiṣẹ́ nínú iṣẹ́ ìránsẹ Pétérù gẹ́gẹ́ bí Àpósítélì sí àwọn Júù, òun kan náà ni ó ṣiṣẹ́ nínú iṣẹ́ ìránsẹ mi gẹ́gẹ́ bí Àpósítélì sí àwọn aláìkọlà.
9. Jákọ́bù, Pétérù, àti Jòhánù, àwọn ẹni tí ó dàbí ọ̀wọ̀n, fún èmi àti Bánábà ni ọwọ́ ọ̀tún ìdàpọ̀ nígbà tí wọ́n rí oore-ọ̀fe tí a fi fún mi, wọ́n sì gbà pé kí àwa náà tọ àwọn aláìkọlà lọ, nígbà ti àwọn náà lọ sọ́dọ̀ àwọn Júù.
10. Ohun gbogbo tí wón bèèrè fún ni wí pé kí a máa rántí àwọn tálákà, ohun kan náà gan-an tí mo ń làkàkà láti ṣe.
11. Ṣùgbọ́n nígbà tí Pétérù wá sí Ańtíókù, mo ta kò ó lójú ara rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ ẹni tí à bá báwí.
12. Nítorí pé kí àwọn kan tí ó ti ọ̀dọ̀ Jákọ́bù wá tó dé, ó ti ń ba àwọn aláìkọlà jẹun; Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n dé, ó fà sẹ́yìn, ó sì ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ kúrò lọ́dọ̀ àwọn aláìkọlà nítorí ó bẹ̀rù àwọn ti ó kọlà.
13. Àwọn Júù tí ó kù pawọ́pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀ lati jùmọ̀ ṣe àgàbàgebè, tó bẹ́ẹ̀ tí wọn sì fi àgàbàgebè wọn si Bánábà lọnà.
14. Nígbà tí mo rí i pé wọn kò rìn déédéé gẹ́gẹ́ bí òtítọ́ ìyìn rere, mo wí fún Pétérù níwájú gbogbo wọn pé, “Bí ìwọ, tí ì ṣe Júù ba ń rìn gẹ́gẹ́ bí ìwà àwọn aláìkọlà, è é ṣe tí ìwọ fi ń fi agbára mu àwọn aláìkọlà láti máa rìn bí àwọn Júù?
15. “Àwa tí i ṣe Júù nípa ìbí, tí kì i sí ì ṣe ‘aláìkọlà ẹlẹ́ṣẹ̀,’