Ẹ́sítà 5:11-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Hámánì gbéraga sí wọn nípa títóbi ọ̀rọ̀ rẹ̀, púpọ̀ àwọn ọmọ rẹ̀, àti gbogbo ọ̀nà tí ọba ti bu ọla fún-un àti bí ó ṣe gbé e ga ju àwọn ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè tó kù lọ.

12. Hámánì tún fi kún-un pé, “Kìí ṣe èyí nìkan. Èmi nìkan ni ayaba Ẹ́sítà pè láti sin ọba wá sí ibi àsè tí ó sè. Bákan náà, ó sì tún ti pè mí pẹ̀lú ọba ní ọ̀la.

13. Ṣùgbọ́n gbogbo èyí kò ì tíì tẹ́ mi lọ́rùn níwọ̀n ìgbà tí mo bá sì ń rí Módékáì aráa Júù yẹn tí ó ń jòkòó lẹ́nu ọ̀nà ọba.”

14. Ìyàwó rẹ̀ Ṣérésì àti àwọn ọ̀rẹ́ẹ rẹ̀ wí fún-un pé, “Ri igi kan, kí ó ga tó ìwọ̀n míta mẹ́ta-lélógún, kí o sì sọ fún ọba ní òwúrọ̀ ọ̀la kí ó gbé Módékáì rọ̀ sórí i rẹ̀. Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọba lọ sí ibi àṣè pẹ̀lú ayọ̀.” Èrò yí dùn mọ́ Hámánì nínú, ó sì ri igi náà.

Ẹ́sítà 5