9. Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀,Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu;olùtùnú kò sì sí fún un.“Wo ìpọ́njú mi, Olúwa,nítorí àwọn ọ̀ta ti borí.”
10. Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ légbogbo ìní rẹ;o rí àwọn ìlú abọ̀rìṣàtí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ—àwọn tí o ti kọ̀ sílẹ̀láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.
11. Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérorabí wọ́n ti ń wá oúnjẹ;wọ́n fi ohun ìní wọn se pàsípààrọ̀ oúńjẹláti mú wọn wà láàyè.“Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó,nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”