Ékísódù 4:21-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Olúwa sì sọ fún Mósè pé, “Ní ìgbà tí ìwọ bá padà sí Éjíbítì rí i pé ìwọ se iṣẹ́ ìyanu ni iwájú Fáráò. Èmi ti fún ọ lágbára láti ṣe é. Èmi yóò sì ṣé àyà rẹ̀ le, òun kì yóò jẹ́ kí àwọn ènìyàn náà kí ó lọ.

22. Lẹ́yìn náà, kí o sọ fún Fáráò pé, ‘Èyí ni Olúwa sọ: Ísírẹ́lì ní àkọ́bí ọmọ mi ọkùnrin,

23. mo sọ fún ọ, “Jẹ́ kí ọmọ mi lọ, ki òun kí ó lè máa sìn mí.” Ṣùgbọ́n ìwọ kọ̀ láti jẹ́ kí ó lọ; nítorí náà, èmi yóò pa àkọ́bí ọmọ rẹ ọkùnrin.’ ”

24. Ní ọ̀nà ìrìnàjò rẹ, ni ibi tí wọ́n gbé sùn ní ilé-èrò ní alẹ́, Olúwa pàdé Mósè, ó sì fẹ́ láti pa á.

Ékísódù 4