Ékísódù 39:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nínú aṣọ aláró, ti elésèé àlùkò àti ti òdòdó ni wọ́n fi ṣe aṣọ híhun fún àwọn òsìsẹ́ ní ibi mímọ́. Ó sì tún dá aṣọ mímọ́ fún Árónì gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mósè.

2. Ó ṣe ẹ̀wù èfòdì wúrà, ti aṣọ aláró, ti elésèé àlùkò, ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára.

3. Ó sì lu wúrà náà di ewé fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, ó sì tún gé e láti fi ṣe iṣẹ́ sí aṣọ aláró, ti elésèé àlùkò, ti òdòdó, àti sínú ọ̀gbọ̀ dáradára ni ti iṣẹ́ ọgbọ́n iṣẹ́ ọnà.

4. Ó ṣe aṣọ èjìká fún ẹ̀wù èfòdì náà, èyí tí ó so mọ igun rẹ̀ méjèèjì, nítorí kí ó lè so pọ̀.

Ékísódù 39