Ékísódù 36:21-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Ọ̀kọ̀ọ̀kan pákó náà jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá ní gíga àti ìgbọ̀nwọ́ kan ààbọ̀ ní fífẹ̀,

22. pẹ̀lú ìtẹ̀bọ̀ méjì tí ó kọjú sí ara wọn. Wọ́n ṣe gbogbo pákó Àgọ́ náà bí èyí.

23. Wọn ṣe ogún pákó sí ìhà gúsù Àgọ́ náà.

24. Wọ́n sì ṣe ogójì (40) fàdákà ihò ìtẹ̀bọ̀ lọ sí ìṣàlẹ̀ wọn ìtẹ̀bọ̀ méjì fún pákó kọ̀ọ̀kan, ọ̀kọ̀ọ̀kan ní ìṣàlẹ̀ ìtẹ̀bọ̀.

25. Fún ìhà kejì, ìhà àríwá Àgọ́ náà, wọ́n ṣe ogún pákó

26. ogójì (40) fàdákà ihò ìtẹ̀bọ̀ méjì ní ìṣàlẹ̀ pákó kọ̀ọ̀kan.

27. Wọ́n ṣe pákó mẹ́fà sì ìkángun, ní ìkangun ìhà ìwọ̀ oòrùn Àgọ́ náà,

28. pákó méjì ni wọ́n ṣe sí igun Àgọ́ náà ní ìkangun.

29. Ní igun méjèèjì yìí, pákó méjì ni ó wà níbẹ láti ìdí dé orí rẹ̀ wọ́n sì kó wọ́n sí òrùka kan; méjèèjì rí bákan náà.

Ékísódù 36