Ékísódù 31:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Olúwa wí fún Mósè pé,

2. “Wò ó, èmi ti yan Bésálélì ọmọ Úrì, ọmọ Húrì, ti ẹ̀yà Júdà,

3. Èmi sì ti fi ẹ̀mí Ọlọ́run kún-un pẹ̀lú ọgbọ́n, agbára àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.

4. Láti se aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,

5. láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.

Ékísódù 31