1. Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mósè ń sọ́ agbo ẹran Jẹ́tírò baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Mídíánì. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jínjìn nínú ihà. Ó dé Hórébù, òkè Ọlọ́run.
2. Níbẹ̀ ni ańgẹ́lì Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́ iná ti ń jó láàrin igbó. Mósè rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run
3. Nígbà náà ni Mósè sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”