10. Ìwọ fẹ́ èèmí rẹòkun ru bò wọ́n mọ́lẹ̀wọ́n rì bí òjéni àárin omi ńlá.
11. “Ta ni nínú àwọn òrìṣà tó dàbí rẹ, Olúwa?Ta ló dàbí rẹ:ní títóbi,ní mímọ́ Ẹlẹ́rù ni yìnTí ń se ohun ìyanu?
12. Ìwọ na apá ọ̀tún rẹIlẹ̀ si gbé wọn mì.
13. “Nínú ìfẹ́ rẹ ti kì í ṣákìíìwọ se amọ̀nàÀwọn ènìyàn náà tí ìwọ ti ràpadàNínú agbára rẹ ìwọ yóò tọ́ wọn lọsí ibi ìjókòó rẹ mímọ́.
14. Orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ wọn yóò wárìrìÌkáàánú yóò mi àwọn ènìyàn palẹ́sítínì.
15. Ìbẹ̀rù yóò mú àwọn ìjòyè Édómù,Àwọn olórí Móábù yóò wárìrìÀwọn ènìyàn Kénánì yóò sì yọ̀ danu;
16. Ìbẹ̀rù-bojo yóò subú lù wọ́n nítorínína títóbi apá rẹ̀wọn yóò dúró jẹ́ ẹ́ láì mira bí i òkútaTítí àwọn ènìyàn rẹ yóò fi ré kọjá, Olúwa,Títí tí àwọn ènìyàn tí o ti rà yóò fi ré kọjá.