5. Kì í se nítorí òdodo yín, tàbí ìdúróṣinṣin ni ẹ ó fí wọ ìlú wọn lọ láti gba ilẹ̀ wọn, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀ èdè wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi lé wọn jáde kúrò níwájú u yín láti lè mú ohun tí ó búra fún àwọn baba ṣẹ: fún Ábúráhámù, Ísáákì àti Jákọ́bù.
6. Ṣùgbọ́n kí ó yé yín pé kì í ṣe nítorí òdodo yín ni Olúwa Ọlọ́run yín fi ń fún un yín ní ilẹ̀ rere náà, láti ní, nítorí pé alágídí ènìyàn ni ẹ jẹ́.
7. Ẹ rántí, ẹ má sì ṣe gbàgbé bí ẹ ti mú Olúwa Ọlọ́run yín bínú ní ihà. Láti ọjọ́ ti ẹ tí kúrò ní Éjíbítì ni ẹ ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa títí tí ẹ fi dé ìhín yìí.
8. Ní Hórébù ẹ mú kí Olúwa bínú, títí débi pé ó fẹ́ run yín.