2. Olúwa Ọlọ́run wa bá wa dá májẹ̀mú ní Hórébù.
3. Kì í ṣe àwọn baba wa ni Olúwa bá dá májẹ̀mú yìí bí kò ṣe àwa, àní pẹ̀lú gbogbo àwa tí a wà láàyè níbí lónìí.
4. Olúwa bá a yín sọ̀rọ̀ lójúkojú láàrin iná lórí òkè.
5. (Ní ìgbà yìí, mo wà láàrin ẹ̀yin pẹ̀lú Ọlọ́run láti sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún un yín torí pé ẹ̀rù Ọlọ́run ń bà yín, ẹ kò sì lè kọjá lọ sórí òkè) Ó sì wí pé:
6. “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti Íjíbitì láti oko ẹrú wá.
7. “Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ní Ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú ù mi.
8. “Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín ní ìrí ohunkóhun lọ́run tàbí ní ilẹ̀ ní ìṣàlẹ̀ níhìn-ín tàbí nínú omi ní ìṣàlẹ̀.
9. Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ foríbalẹ̀ láti sìn wọ́n. Torí pé èmi Olúwa Ọlọ́run yín Ọlọ́run owú ni mí, tí í fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ baba jẹ ọmọ títí dé ìran kẹ́ta àti ẹ̀kẹ́rin ní ti àwọn tí ó kórìíra mi.