2. Olúwa Ọlọ́run wa bá wa dá májẹ̀mú ní Hórébù.
3. Kì í ṣe àwọn baba wa ni Olúwa bá dá májẹ̀mú yìí bí kò ṣe àwa, àní pẹ̀lú gbogbo àwa tí a wà láàyè níbí lónìí.
4. Olúwa bá a yín sọ̀rọ̀ lójúkojú láàrin iná lórí òkè.
5. (Ní ìgbà yìí, mo wà láàrin ẹ̀yin pẹ̀lú Ọlọ́run láti sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún un yín torí pé ẹ̀rù Ọlọ́run ń bà yín, ẹ kò sì lè kọjá lọ sórí òkè) Ó sì wí pé: