Deutarónómì 4:26-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. Mo pe ọ̀run àti ayé láti jẹ́rìí takò yín lónìí, pé kíákíá ni ẹ ó parun ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń la Jọ́dánì kọjá lọ láti gbà. Ẹ kò ní pẹ́ ní ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò run pátapáta.

27. Olúwa yóò fọ́n-ọn yín ká sí àárin àwọn ènìyàn náà, àwọn díẹ̀ nínú un yín ni yóò yè láàrin orílẹ̀ èdè tí Olúwa yóò fọ́n ọn yín sí.

28. Ẹ ó sì máa sin Ọlọ́run tí àwọn ènìyàn fi ọwọ́ ṣe: tí wọ́n fi igi àti òkúta ṣe, èyí tí kò le ríran, gbọ́rọ̀, jẹun tàbí gbọ́ òórùn.

29. Bí ẹ̀yin bá wá Olúwa Ọlọ́run yín láti bẹ̀ẹ́ ẹ ó ri i, bí ẹ bá wá a, pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà a yín.

30. Bí ẹ bá wà nínú wàhálà, bí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ṣẹlẹ̀ sí yín, láìpẹ́ ẹ ó tún padà tọ Olúwa Ọlọ́run yín wá, ẹ ó sì gbọ́ tirẹ̀.

Deutarónómì 4