Deutarónómì 3:6-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Gbogbo wọn ni a parun pátapáta gẹ́gẹ́ bí á ti ṣe sí Síhónì ọba Hésíbónì, tí a pa gbogbo ìlú wọn run pátapáta: tọkùnrin tobìnrin àti àwọn ọmọ wọn.

7. Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀ṣìn àti ìkógún àwọn ìlú wọn, fún ara wa.

8. Ní ìgbà náà ni a ti gba ilẹ̀ tí ó wà ní Jọ́dánì láti odò Ánónì, títí dé orí òkè Hámónì lọ́wọ́ àwọn ọba Ámórì méjèèjì wọ̀nyí.

9. (Àwọn ará Sídónì ń pe Hámónì ní Sírónì: Àwọn Ámórì sì ń pè é ní Sénírì)

10. Gbogbo àwọn ìlú tí o wà ní orí òkè olórí títẹ́ náà ni a gbà àti gbogbo Gílíádì, àti gbogbo Báṣánì, títí dé Ṣálékà, àti Édíréì, ìlú àwọn ọba Ógù ní ilẹ̀ Báṣánì.

11. (Ógù tí í ṣe ọba Báṣánì nìkan ni ó ṣẹ́kù nínú àwọn ará Ráfátì. Ibùsùn rẹ̀ ni a fi irin ṣe, ó sì gùn ju ẹsẹ̀ bàtà mẹ́tàlá lọ ní gígùn àti ẹsẹ̀ bàtà mẹ́fà ní ìbú. Èyí sì wà ní Rábà ti àwọn Ámórì.)

Deutarónómì 3