8. Nítorí tí o rí àbùkù lára wọn, ó wí pé,“Kíyèsí i ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí,ti èmi o bá ilé Ísírẹ́lìàti ilé Júdà dá májẹ̀mu títún.
9. Kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí májẹ̀mútí mo ti bá àwọn baba baba wọn dá,nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́ láti mú wọn jádekúrò ní Íjíbítì, nítorí wọn kò jẹ́ olótítọ́ sí májẹ̀mú mièmi kò sì ta wọ́n nu, ni Olúwa wíni Olúwa wí.
10. Nítorí èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Ísírẹ́lìdá lẹ̀yìn àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, ni Olúwa wí.Èmi ó fi òfin mi sí inú wọn,èmi ó sì kọ wọ́n sí ọkàn wọn,èmi ó sì máa jẹ́ Ọlọ́run fún wọn,wọn ó sì máa jẹ́ ènìyàn fún mi.