Ámósì 7:2-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Nígbà tí wọ́n jẹ koríko ilẹ̀ náà mọ́ féfé nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Ọlọ́run, mo bẹ̀ ọ́, dáríjìn! Báwo ni Jákọ́bù yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”

3. Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí;“Èyí kò ni sẹlẹ̀,” ni Olúwa wí.

4. Èyí ni ohun ti Olúwa Ọlọ́run fi hàn mí: Olúwa Ọlọ́run ń pè fún ìdájọ́ pẹ̀lú iná; ó jó ọ̀gbun ńlá rún, ó sì jẹ ilẹ̀ run.

5. Nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Ọlọ́run jọ̀wọ́ má ṣe ṣe é! Báwo ni Jákọ́bù yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”

6. Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí.“Èyí náà kò ní ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa alágbára wí

Ámósì 7