7. Nitorí náà, àwọn ni yóò lọ sí ìgbèkùnpẹ̀lú àwọn tí ó ti kó lọ sí ìgbèkùnàwẹ̀jẹwẹ̀mú àwọn tí ń ṣe àṣelékè ni a ó mú kúrò
8. Olúwa ọ̀gá ògo ti búra fúnra rẹ̀ Olúwa Ọlọ́run alágbára sì ti wí pé:“Mo kórìíra ìgbéraga Jákọ́bùn kò sì ní inú dídùn sí odi alágbára rẹ̀Èmi yóò sì fa ìlú náà lé wọn lọ́wọ́àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.”
9. Bí Ọkùnrin mẹ́wàá bá sẹkù nínú ile kan, àwọn náà yóò kú
10. Bí ẹbí tí ó yẹ kí ó gbé òkú wọn jáde fún sínsin bá wọlé, bí o ba sì béérè pé ǹjẹ́ ẹnìkan wa tí ó farapamọ́ níbẹ̀, “Njẹ ẹnìkankan wà lọ́dọ̀ yín?” tí ó bá sì dáhùn wí pé, “Rárá,” nígbà náà ni yóò wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́ àwa kò gbọdọ̀ dárúkọ Olúwa.”