Ámósì 6:3-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ẹ̀yin sún ọjọ́ ibi síwájú,ẹ sì mú ìjọba òǹrorò súnmọ́ tòòsí

4. Ẹ̀yin sùn lé ibusùn tí a fi eyín erin ṣeẸ sì tan ara sílẹ̀ ni orí àwọn ibùsùnẸ̀yin pa èyí tí o dára nínú àwọn ọ̀dọ́ àgùntàn yín jẹẸ sì ń pa àwọn ọ̀dọ́ màlúù láàrin agbo wọn jẹ

5. Ẹ̀yin ń lo ohun èlò orin bí i DáfídìẸ sì ń ṣe àwọn àpilẹ̀rọ̀ àwọn ohun èlò orin

6. Ẹ̀yín mu wáìnì ẹ̀kún ọpọ́n kanàti ìkunra tí o dára jùlọṢùgbọ́n ẹ̀yin kò káànú ilé Jósẹ́fù tí o di ahoro

7. Nitorí náà, àwọn ni yóò lọ sí ìgbèkùnpẹ̀lú àwọn tí ó ti kó lọ sí ìgbèkùnàwẹ̀jẹwẹ̀mú àwọn tí ń ṣe àṣelékè ni a ó mú kúrò

8. Olúwa ọ̀gá ògo ti búra fúnra rẹ̀ Olúwa Ọlọ́run alágbára sì ti wí pé:“Mo kórìíra ìgbéraga Jákọ́bùn kò sì ní inú dídùn sí odi alágbára rẹ̀Èmi yóò sì fa ìlú náà lé wọn lọ́wọ́àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.”

9. Bí Ọkùnrin mẹ́wàá bá sẹkù nínú ile kan, àwọn náà yóò kú

10. Bí ẹbí tí ó yẹ kí ó gbé òkú wọn jáde fún sínsin bá wọlé, bí o ba sì béérè pé ǹjẹ́ ẹnìkan wa tí ó farapamọ́ níbẹ̀, “Njẹ ẹnìkankan wà lọ́dọ̀ yín?” tí ó bá sì dáhùn wí pé, “Rárá,” nígbà náà ni yóò wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́ àwa kò gbọdọ̀ dárúkọ Olúwa.”

Ámósì 6