13. Ẹ̀yin yọ̀ torí ìṣẹ́gun lórí LódábárìẸ̀yin sì wí pé, “Ṣé kì í se agbára wa ni àwa fi gba Kánáímù?”
14. Nítorí Olúwa Ọlọ́run alágbára wí pé,“Èmi yóò gbé orílẹ̀-èdè kan dìde sí ọ ìwọ Ísírẹ́lì,tí yóò máa ni ọ́ lára ní gbogbo ọ̀nàláti ẹnu ọ̀nà ìwọlé Hámátì títí dé àfonífojì aginjù.”