Ámósì 5:7-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ẹ̀yin tí ẹ̀ sọ òdodo di ìkoròTí ẹ sì gbé olódodo ṣánlẹ̀

8. Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Píláédì àti ÓríónìẸni tí ó sọ òru dúdú di òwúrọ̀Tí ó sọ ọjọ́ dúdú di ìmọ́lẹẸni tí ó wọ́ omi òkun jọpọ̀Tí ó sì rọ̀ wọ́n sí orí ilẹ̀ Olúwa ni orúkọ rẹ̀,

9. Ó fọ́n ìparun sí ìlú olódiTí ó sì sọ àwọn ibùgbé àwọn ọmọ aládé di ahoro

10. Ìwọ kórìíra ẹni tí ń ṣòdì ní ẹnu ibodèó sì ń pẹ̀gàn ẹni tí ń sọ òtítọ́

11. Ìwọ ń tẹ talákà mọ́lẹ̀o ń fi ipá gba ọkà lọ́wọ́ wọnNítorí náà, ìwọ ti fi òkúta tí a gbẹ́ kọ́léṣùgbọ́n ẹ kò sì ní gbé inú wọnNítòótọ́ ìwọ ti gbin ọgbà àjàrà tí ó lẹ́wà.Ìwọ kò ní mu wáìnì inú wọn

Ámósì 5