Ámósì 5:10-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Ìwọ kórìíra ẹni tí ń ṣòdì ní ẹnu ibodèó sì ń pẹ̀gàn ẹni tí ń sọ òtítọ́

11. Ìwọ ń tẹ talákà mọ́lẹ̀o ń fi ipá gba ọkà lọ́wọ́ wọnNítorí náà, ìwọ ti fi òkúta tí a gbẹ́ kọ́léṣùgbọ́n ẹ kò sì ní gbé inú wọnNítòótọ́ ìwọ ti gbin ọgbà àjàrà tí ó lẹ́wà.Ìwọ kò ní mu wáìnì inú wọn

12. Nítorí mo mọ iye àìṣedédé rẹmo sì mọ bí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tí tóbi tó.Ìwọ ni olódodo lára, ìwọ sì ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀o sì ń fi òtítọ́ du talákà ní ilé ẹjọ́

13. Àwọn ọlọgbọ́n máa ń dákẹ́ jẹ́ẹ́ ní àkókò wọ̀nyíNítorí búburú ni gbogbo ọjọ́.

14. Wá rere, má ṣe wá búburúkí ìwọ ba à le yèNígbà náà ni Olúwa alágbára yóò wà pẹ̀lú ù rẹ.Òun yóò sì wà pẹ̀lú ù rẹ bí ìwọ ṣe wí

Ámósì 5