8. Èmi yóò ké àwọn olùgbé Ásódì kúrò.Àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Ákélónì mú.Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ékírónìtítí tí ìyókù Fílístínì yóò fi ṣègbé,”ni Olúwa Ọlọ́run wí.
9. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tírèàní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà.Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbékùn fún ÉdómùWọn kò sì nán-án-ní májẹ̀mú ọbàkan,
10. Èmi yóò rán iná sí ara odi TírèTí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”
11. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Édómù,àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padàNítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀,Ó sì gbé gbogbo àánú sọnùìbínú rẹ̀ sì ń faniya títíó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́
12. Èmi yóò rán iná sí orí TémánìTí yóò jó gbogbo ààfin Bósírà run.”
13. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ámónìàní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gílíádìkí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.