12. Àwọn Árámínì láti ìlà-oòrùnàti Fílístínì láti ìwọ̀ oòrùnwọ́n si fi gbogbo ẹnu jẹ́ Ìsirẹli runNí gbogbo èyí ìbínú un rẹ̀ kò yí kúròṢùgbọ́n ọwọ́ rẹ̀ nà jáde ṣíbẹ̀.
13. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò tí ì yípadàsí ẹni náà tí ó lù wọ́nbẹ́ẹ̀ ní wọ́n kò wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
14. Nítorí náà ni Olúwa yóò ṣe ké àti orí àti ìrùkúrò ní Ísírẹ́lì,àti Imọ̀-ọ̀pẹ àti koríko-odò ní ọjọ́ kanṣoṣo,
15. Àwọn alàgbà, àti àwọn gbajúmọ̀ ni orí,àwọn wòlíì tí ń kọ́ni ní irọ́ ni ìrù.
16. Àwọn tí ó ń tọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí sì wọ́n lọ́nàÀwọn tí a sì tọ́ ni a ń sin sí ìparun.