Àìsáyà 66:2-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Kì í ha á ṣe ọwọ́ mi ló tí ṣe nǹkan wọ̀nyí,bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì wà?”ni Olúwa wí.“Eléyìí ni ẹni tí mo kà sí:ẹni náà tí ó rẹrarẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì kẹ́dùn ní ọkàn rẹ̀,tí ó sì wárìrì nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ mi.

3. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fi akọ màlúù rúbọó dàbí ẹni tí ó pa ènìyàn kanàti ẹni tí ó bá fi ọ̀dọ́ àgùntàn kan tọrẹ,dàbí ẹni tí ó kán ajá kan lọ́rùn;ẹnikẹ́ni tí ó bá fi irúgbin oníhóró tọrẹdàbí ẹni tí ó mú ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ wá,ẹni tí ó bá sì ṣun tùràrí ìrántí,dàbí ẹni tí ó sin ère òrìṣà.Wọ́n ti yan ipa ọ̀nà tiwọn,ọkàn wọn pẹ̀lú sì láyọ̀ nínú ohun ìríra wọn;

4. Fún ìdí èyí ni èmi pẹ̀lú yóò ṣe fi ọwọ́ líle mú wọnn ó sì mú ohun tí wọ́n bẹ̀rù rẹ̀ wá sórí wọn.Nítorí nígbà tí mo pè, kò sí ẹni tí ó dáhùn,nígbà tí mo sọ̀rọ̀, ẹnikẹ́ni kò tẹ́tísílẹ̀.Wọ́n ṣe ohun búburú ní ojú miwọ́n sì yan ohun tí mo kóríìra rẹ̀.”

Àìsáyà 66