Àìsáyà 64:5-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Ìwọ a máa wá fún ìrànlọ́wọ́ àwọn tí wọnń fi ayọ̀ ṣe ohun tótọ́,tí ó rántí ọ̀nà rẹ.Ṣùgbọ́n nígbà tí a bẹ̀rẹ̀ sí dẹ́ṣẹ̀ sí wọn,inú bí ọ.Báwo ni a ó ṣe gbà wá là?

6. Gbogbo wa ti dàbí ẹnìkan tí ó jẹ́ aláìmọ́,gbogbo òdodo wa sì dàbí èkíṣà ẹlẹ́gbin;gbogbo wa kákò bí ewé,àti bí afẹ́fẹ́, ẹ̀ṣẹ̀ wa ti gbá wa lọ kúrò.

7. Ẹnikẹ́ni kò pe orúkọ rẹtàbí kí ó gbìyànjú láti dì ẹ́ mú;nítorí ìwọ ti fi ojú rẹ pamọ́ fún waó sì jẹ́ kí àwa ṣòfò dànù nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa.

8. Ṣíbẹ̀ ṣíbẹ̀, Olúwa, ìwọ ni Baba wa.Àwa ni amọ̀, ìwọ ni ọ̀mọ;gbogbo wa jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.

9. Má ṣe bínú kọjá ààlà, Ìwọ Olúwa:Má ṣe rántíi gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wa títí láé.Jọ̀wọ́, bojú wò wá, ni a gbàdúrà,nítorí ènìyàn rẹ ni gbogbo wa.

10. Àwọn Ìlú Mímọ́ rẹ ti di aṣálẹ̀;Ṣíhónì pàápàá aṣálẹ̀ ni, Jérúsálẹ́mù ibi ìkọ̀sílẹ̀.

11. Tẹ́ḿpìlì Mímọ́ ológo wa, níbi tí àwọn baba wa ti yìn ọ́,ni a ti fi iná sun,àti ohun gbogbo tí í ṣe ìṣúra wa ti dahoro.

Àìsáyà 64