Àìsáyà 51:19-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Àjálù ìlọ́po ìlọ́po yìí ti dé bá ọ—ta ni yóò tù ọ́ nínú?Ìparun àti Ìdahoro, ìyàn àti idàta ni yó pẹ̀tù sí ọ lọ́kàn?

20. Àwọn ọmọkùnrin rẹ ti dákú;wọ́n sùn sí oríta gbogbo òpópónà,gẹ́gẹ́ bí ẹtu tí a dé mọ́nú àwọ̀n.Ìbínú Olúwa ti kún inú un wọn fọ́fọ́ọ́fọ́àti ìbáwí Ọlọ́run yín.

21. Nítorí náà ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí a ti ṣẹ́ níṣẹ̀ẹ́,tí ọtí ń pa, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún wáìnì

22. Ohun tí Olúwa yín Alágbára jùlọ wí nìyìí,Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó ń pa ènìyàn an rẹ̀ mọ́“Kíyèsí i, mo ti mú un kúrò ní ọwọ́ọ̀ rẹkọ́ọ̀bù tí ó mú ọ ta gbọ̀ngbọ̀nọ́n;láti inú kọ́ọ̀bù náà, ẹ̀kan ìbínú mi,ni ìwọ kì yóò mu mọ́.

23. Èmi yóò fi lé àwọn apọ́nnílójú rẹ lọ́wọ́,àwọn tí ó wí fún ọ pé,‘Dọ̀bálẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí a ó fi máa rìn lóríì rẹ.’Ìwọ náà ṣe ẹ̀yìn rẹ gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀gẹ́gẹ́ bí òpópónà láti máa rìn lóríi rẹ̀.”

Àìsáyà 51