Àìsáyà 48:17-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Èyí ni ohun tí Olúwa wíOlùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ Ísírẹ́lì:“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,tí ó kọ́ ọ ní ohun tí ó dára fún ọ,tí ó tọ́ ọ ṣọ́nà tí ó yẹ kí o máa rìn.

18. Bí ó bá ṣe pé ìwọ bá ti tẹ́tísílẹ̀ sí àṣẹ mi,àlàáfíà rẹ kì bá ti dàbí ì ti odò,àti òdodo rẹ bí ìgbì òkun.

19. Àwọn ọmọ rẹ ìbá ti dàbí i yanrìn,àwọn ọmọ yín bí i horo ọkà tí a kò lè kà tán;orúkọ wọn ni a kì yóò ké kúròtàbí kí a pa wọ́n run níwájú mi.”

20. Fi Bábílónì sílẹ̀,sá fún àwọn ará Bábílónì,ṣe ìfilọ̀ èyí pẹ̀lú ariwo ayọ̀kí o sì kéde rẹ̀.Rán an jáde lọ sí òpin ilẹ̀ ayé;wí pé, “Olúwa ti dá ìránṣẹ́ rẹ̀ Jákọ́bù nídè.”

Àìsáyà 48