13. Níbo ni ọba Hámátì wà, ọba Ápádì, ọba Ìlú Ṣefáfíámù tàbí Hénà tàbí Ífà?”
14. Heṣekáyà gba ìwé náà lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ ó sì kà á. Lẹ́yìn náà ni ó gòkè lọ sí tẹ́ḿpìlì Olúwa ó sì tẹ́ ìwé náà sílẹ̀ níwájú Olúwa.
15. Heṣekáyà sì gbàdúrà sí Olúwa:
16. Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, tí ó gúnwà láàrin àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lóríi gbogbo ìjọba orílẹ̀ ayé. Ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
17. Tẹ́tí sílẹ̀, Ìwọ Olúwa, kí o gbọ́, ya ojú rẹ, Ìwọ Olúwa, kí o rí i; tẹ́tí sí gbogbo ọ̀rọ̀ tí Ṣenakérúbù rán láti fi àbùkù kan Ọlọ́run alààyè.