Àìsáyà 32:10-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Ní ó lé díẹ̀ ní ọdún kanẹ̀yin tí ọkàn an yín balẹ̀ yóò wárìrì;ìkóórè àjàrà kò ní múnádóko,bẹ́ẹ̀ ni ìkóórè èṣo kò ní sí.

11. Wárìrì, ẹ̀yin obìnrin onítẹ̀lọ́rùnbẹ̀rù, ẹ̀yin ọ̀dọ́mọbìnrin tí ẹ rò pé ọkàn yín balẹ̀!Ẹ bọ́ aṣọ yín kúrò,ẹ ró aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ẹ yín.

12. Ẹ lu ọmú un yín fún pápá ìgbádùn náà,fún àwọn àjàrà eléso

13. àti fún ilẹ̀ àwọn ènìyàn miilẹ̀ tí ó ti kún fún ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n—bẹ́ẹ̀ ni, kẹ́dùn fún gbogbo ilé ìturaàti fún ìlú àríyá yìí.

14. Ilé olódi ni a ó kọ̀ sílẹ̀,ìlù aláriwo ni a ó kọ̀tì;ilé olódi àti ilé ìṣọ́ ni yóò di ìdànù títí láéláé,ìdùnnú àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti pápáoko fún àwọn ẹran ọ̀sìn,

15. títí a ó fi tú Ẹ̀mí sí wa lórí láti òkè wá,àti ti aṣálẹ̀ tí yóò dí pápá oko ọlọ́ràáàti tí pápá ọlọ́ràá yóò dàbí ẹgàn.

Àìsáyà 32