Àìsáyà 3:6-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínu àwọnarákùnrin rẹ̀ múnínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé,“Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa,sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”

7. Ṣùgbọn ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé,“Èmi kò ní àtúnṣe kan.Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ò ní aṣọ nílé,ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”

8. Jérúsálẹ́mù ń ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́nJúdà ń ṣubú lọ,ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa,láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.

9. Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn,wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sódómù;wọn ò fi pamọ́!Ègbé ni fún wọn!Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.

Àìsáyà 3