Àìsáyà 29:11-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Fún un yín gbogbo ìran yìí kò yàtọ̀ sí àwọn ọ̀rọ̀ tí a fi èdìdì dì sínú ìwé kíká. Bí ẹ bá sì fún ẹni tí ó lè ka ìwé kíká náà, tí ẹ sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò lè kà á; a ti dì í ní èdìdì.”

12. Tàbí bí ẹ bá fún ẹni tí kò lè ka ìwé kíká náà tí ẹ sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n kà.”

13. Olúwa wí pé:“Àwọn ènìyàn yìí súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹnu wọnwọ́n sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ètè wọn,ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnnà sí mi.Ìsìn wọn fún mini a gbé ka orí òfin tí àwọnọkùnrin kọ́ ni.

14. Nítorí náà lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò yaàwọn ènìyàn yìí lẹ́nupẹ̀lú ìyanu lórí ìyanu;ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ni yóò ṣègbé,ìmọ̀ àwọn onímọ̀ ni yóò pòórá.”

15. Ègbé ni fún àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbunláti fi ètò wọn pamọ́ kúrò lójú Olúwa,tí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ẹ wọn nínú òkùnkùntí wọ́n sì rò pé,“Ta ló rí wa? Ta ni yóò mọ̀?”

Àìsáyà 29