Àìsáyà 26:15-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ìwọ ti mú orílẹ̀ èdè gbòòrò, Olúwa;ìwọ ti mú orílẹ̀ èdè bí sí i.Ìwọ ti gba ògo fún araàrẹ;ìwọ ti sún gbogbo àwọn ààlà ilẹ̀ ṣẹ́yìn.

16. Olúwa, Wọ́n wá sọ́dọ̀ rẹ nínú ìpọ́njúu wọn;nígbà tí o jẹwọ́n ní ìyà,wọ́n tilẹ̀ fẹ́ ẹ̀ má le gbàdúrà kẹ́lẹ́ kẹ́lẹ́.

17. Gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó lóyún tí ó sì fẹ́rẹ bímọtí í rúnra tí ó sì ń sunkún nínú ìrora rẹ̀,bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwa rí níwájúu rẹ Olúwa.

18. Àwa wà nínú oyún, a wà nínú ìroraṣùgbọ́n, afẹ́fẹ́ ni a bí lọ́mọ.Àwa kò mú ìgbàlà wá sí ilẹ̀ ayé;àwa kọ́ ni a bí àwọn ènìyàn tí ó wà láyé.

19. Ṣùgbọ́n àwọn òkúu yín yóò wà láàyèara wọn yóò dìde.Ìwọ tí o wà nínú erùpẹ̀,dìde nílẹ̀ kí o sì ké igbe ayọ̀.Ìrì rẹ dàbí ìrì òwúrọ̀,ayé yóò bí àwọn òkúu rẹ̀ lọ́mọ.

Àìsáyà 26