Àìsáyà 23:6-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Kọjá wá sí Táṣíṣì;pohùnréré, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣù.

7. Ǹjẹ́ èyí náà ni ìlú àríyáa yín,ògbólógbòò ìlú náà,èyí tí ẹṣẹ̀ rẹ̀ ti sìn ín lọláti lọ tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí ó jìnnà réré.

8. Ta ló gbérò èyí sí Tírè,ìlú aládé,àwọn oníṣòwò ẹni tí ó jẹ́ ọmọ aládétí àwọn oníṣòwò o wọ́n jẹ́ ìlúmọ̀míkání orílẹ̀ ayé?

9. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti ṣètò rẹ̀,láti tẹrí ìgbéraga àti ògo rẹ baàti láti rẹ gbogbo àwọn ọlọ́láilé ayé sílẹ̀.

10. Tu ilẹ̀ rẹ gẹ́gẹ́ bí i ti ipadò Náì,Ìwọ ọmọbìnrin Táṣíṣì,nítorí ìwọ kò ní èbúté mọ́.

Àìsáyà 23