Àìsáyà 10:24-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Nítorí náà, báyìí ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí,“Ẹ̀yin ènìyàn mi tí ó ń gbé Ṣíhónì,Ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn Ásíríà,tí ó ń fi ọ̀pá lù yín,tí wọ́n sì ń gbé ọ̀gọ tìyín bíÉjíbítì ti ṣe.

25. Láìpẹ́, ìbínú mi síi yín yóò wá sí òpinn ó sì dojú ìrunú mi kọ wọ́n,fún ìparun wọn.”

26. Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò nà wọ́n ní ẹgba.Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe lu Mídíánìní òkè Órébù,yóò sì gbé ọ̀páa rẹ̀ lé orí omigẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Éjíbítì.

27. Ní ọjọ́ náà, a ó gbé ẹrùu wọn kúrò ní èjìká a yín,àti àjàgà a wọn kúrò ní ọrùn un yína ó fọ́ àjàgà náà,nítorí pé ẹ̀yin ó ti sanra.

28. Wọ́n wọ Áíyátì,Wọ́n gba Mígírónì kọjáWọ́n kó nǹkan pamọ́ sí Mísímásì.

29. Wọ́n ti rékọjá ọ̀nà, wọ́n wí pé,“Àwa ó tẹ̀dó sí Gébà lóru yìí.”Rámà mì tìtìGíbíà ti Ṣọ́ọ̀lù sá lọ.

30. Kígbe ṣókè, ìwọ ọmọbìnrin GálímùDẹtísílẹ̀, Ìwọ LáíṣàÒpè Ánátótì.

Àìsáyà 10